Proverbs 21

1Ọkàn ọba ń bẹ lọ́wọ́ Olúwa;
a máa darí rẹ̀ lọ ibi tí ó fẹ́ bí ipa omi.

2Gbogbo ọ̀nà ènìyàn dàbí i pé ó dára lójú rẹ̀
ṣùgbọ́n, Olúwa ló ń díwọ̀n ọkàn.

3Ṣíṣe ohun tí ó dára tí ó sì tọ̀nà
ó ṣe ìtẹ́wọ́gbà sí Olúwa ju ẹbọ lọ.

4Ojú tí ó gbéga àti ọkàn ìgbéraga,
ìmọ́lẹ̀ àwọn ènìyàn búburú, ẹ̀ṣẹ̀ ni!

5Ètè àwọn olóye jásí èrè
bí ìkánjú ṣe máa ń fa òsì kíákíá.

6Ìṣúra tí a kójọ nípasẹ̀ ahọ́n tí ń parọ́
jẹ́ ìrì lásán àti ìkẹ́kùn ikú.

7Ìwà ipá àwọn ènìyàn búburú yóò wọ́ wọn lọ,
nítorí wọ́n kọ̀ láti ṣe ohun tí ó tọ́.

8Ọ̀nà ẹlẹ́ṣẹ̀ kún fún ìwà ẹ̀ṣẹ̀
ṣùgbọ́n iṣẹ́ onínú funfun jẹ́ títọ́.

9Ó sàn láti máa gbé ní kọ̀rọ̀ orí òrùlé
ju láti ṣe àjọpín ilé pẹ̀lú aya oníjà.

10Ènìyàn búburú ń fẹ́ ibi
aládùúgbò rẹ̀ kì í rí àánú kankan gbà lọ́dọ̀ rẹ̀.

11Nígbà tí a bá ń fìyà jẹ ẹlẹ́gàn,
òpè a máa kọ́gbọ́n,
nígbà tí a bá sì kọ́ ọlọ́gbọ́n yóò ní ìmọ̀.

12Olódodo ṣàkíyèsí ilé ènìyàn búburú
ó sì mú ènìyàn búburú wá sí ìparun.

Ìṣúra ẹni tí o gbọ́n

13Ẹnikẹ́ni tí ó bá ti di etí rẹ̀ sí igbe olùpọ́njú,
òun tìkára rẹ̀ yóò ké pẹ̀lú;
ṣùgbọ́n a kì yóò gbọ́.

14Ọ̀rẹ́ ìkọ̀kọ̀, mú ìbínú kúrò:
àti owó àbẹ̀tẹ́lẹ̀ láti ibi ìkọ̀kọ̀ wá,
dẹ́kun ìbínú líle.

15Ayọ̀ ni fún olódodo láti ṣe ìdájọ́:
ṣùgbọ́n ìparun ni fún àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀.

16Ẹni tí ó bá yà kúrò ní ọ̀nà òye,
yóò máa gbé inú ìjọ àwọn òkú.

17Ẹni tí ó bá fẹ́ afẹ́, yóò di tálákà:
ẹni tí ó fẹ́ ọtí wáìnì pẹ̀lú òróró kò le lọ́rọ̀.

18Ènìyàn búburú ni yóò ṣe owó ìràpadà fún olódodo,
àti olùrékọjá fún ẹni dídúró ṣinṣin.

19Ó sàn láti jókòó ní aginjù ju pẹ̀lú
oníjà obìnrin àti òṣónú lọ.

20Ìṣúra iyebíye àti òróró wà ní ibùgbé ọlọ́gbọ́n;
ṣùgbọ́n òmùgọ̀ ènìyàn n bà á jẹ́.

21Ẹni tí ó bá tẹ̀lé òdodo àti àánú yóò rí ìyè,
òdodo, àti ọlá.

22Ọlọ́gbọ́n gòkè odi ìlú àwọn alágbára,
ó sì bi ibi gíga agbára ìgbẹ́kẹ̀lé wọn ṣubú.

23Ẹnikẹ́ni tí ó bá pa ẹnu àti ahọ́n rẹ̀ mọ́,
ó pa ọkàn rẹ̀ mọ́ kúrò nínú ìyọnu.

24Agbéraga àti alágídí ènìyàn ń gan orúkọ ara rẹ̀ nítorí ó ń hùwà nínú ìwà ìgbéraga rẹ̀,
àti nínú ìbínú púpọ̀púpọ̀.

25Ẹlẹ́rìí èké yóò ṣègbé, àwọn tí ó gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ̀ yóò parun láé;
nítorí tí ọwọ́ rẹ̀ kọ iṣẹ́ ṣíṣe.
26Ó ń fi ìlara ṣe ojúkòkòrò ní gbogbo ọjọ́:
ṣùgbọ́n olódodo a máa fi fún ni kì í sì í dáwọ́ dúró.

27Ẹbọ ènìyàn búburú, ìríra ni:
mélòó mélòó ni nígbà tí ó mú un wá pẹ̀lú èrò ìwà ibi?

28Ẹlẹ́rìí èké yóò ṣègbé:
ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ ẹni tí ó gbọ́, yóò dúró.

29Ènìyàn búburú mú ojú ara rẹ̀ le:
ṣùgbọ́n ẹni ìdúró ṣinṣin ni ó ń mú ọ̀nà rẹ̀ tọ́.

30Kò sí ọgbọ́n, kò sí ìmòye,
tàbí ìmọ̀ràn tí ó le mókè níwájú Olúwa.

31A ń múra ẹṣin sílẹ̀ de ọjọ́ ogun:
ṣùgbọ́n ìṣẹ́gun jẹ́ ti Olúwa.
Copyright information for YorBMYO